
Gẹ́gẹ́ bíi odò ni omi ojú ṣe ń sàn ní ìlú Ògbómọ̀ṣọ́ lẹ́nu lọ́ọ́lọ́ọ́ yìí nibi tí àṣírí ikú ti ó pa ọkunrin gbajúgbajà oníṣòwò hóró kan Alhaji Wasiu Àdìgún ti tú tí wọn sì wú òkú rẹ̀ jáde lábẹ́ àgbàdo tí wọ́n bò ó mọ́.
Naija notes Yorùbá gbọ́ pé ọmọ àǹtí rẹ̀ ti ó ń gbé ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ló lù ú ní igi pa látẹ̀yìn pẹ̀lú ète àtigbé òbìtìbítí mílíọ̀nù náírà tí wọ́n gbé fún Alhaji Wasiu láti ra káṣú lọ .

Ní kété tí ó ṣe iṣẹ́ burúkú yìí tan, tí ó sì bo òkú rẹ̀ mọ́ inú àgbàdo, ló wá gbé àtowó àti mọ́tò olóògbé sá lọ tí ẹnikẹ́ni kò sí mọ ibi ti ó wà titi di asiko ti a ń kó ìròyìn yìí jọ.
Lẹyìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ tí wọ́n ti ń wa ọkùnrin yìí ni wón tó rí i nínú àgbàdo.Won ti fi òrò náà tó àwọn agbófinró létí.
Ènìyàn dáradàra ni Alhaji Wasiu Àdìgún nígbà ayé rẹ̀.Òun sì ní alága àwọn tó ń ra hóró kaṣú, àgbàdo,jéró àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ ní ìlú Ògbómọ̀ṣọ́ àti agbègbè rẹ̀.

Oyè Oyèdọ̀tun jẹ́ gbajúgbajà Agbóhùnsáfẹ́fẹ́ Oníròyìn,Akéwì,Olórin,Ọ̀ǹkọ̀wé, àti Ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn.Ìfẹ́ rẹ̀ sí iṣẹ́ ìròyìn àti èdè Yorùbá ló fa ìdásílẹ̀ ìkànnì yìí.A ti fi ìkòkò ṣe ọbẹ̀,ó yá ẹ je ká tọ́ ọ wò..Oyinmọmọ!

Ẹ kú isẹ takuntakun ẹ̀gbọ́n mi. Yóò máa jú waá ṣe o lágbára Ọlọ́run Olódùmarè.