Ikú pa Doyin Òkúpè:Ìpẹ́ru Mì tìtì

Lójijì ní ìròyìn tàn kiri ní kùtùkùtù òwúrò òní pé ògbóhùntarigì olóṣèlú nnì Doyin Òkúpè di olóògbé.

Ó ti tó ọjọ́ mẹ́tà tí ó ti ń wàyá ìjà pẹ̀lú àrùn jẹjẹrẹ; ìgbàgbọ sì ni pé àisàn náà ló gba ẹ̀mí rẹ̀.

Ọmọ bíbí ìlú Ìpẹ́ru ni ìpínlẹ̀ Ògùn ni Òkúpè.Ẹni ọdún méjìléláàádọ́rin ní í ṣe.Ó ti fìgbà kan rí jẹ́ Olùbádámọ̀ràn pàtàkì sí Ààrẹ Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́,Atiku Abubakar àti olùdarí àgbà fún ètò ìpolongo Peter Obi nígbà tó ń díje fún ipò Ààrẹ lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú Labour Party ní ọdún 2023.

Àtẹ̀jáde kan ti ó ti ọwọ́ àwọn Mọ̀lẹ́bí olóògbé jáde ló fi ìdí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀.Ki Olúwa kó tẹ́ ẹ sí afẹ́fẹ́ rere.

Leave a Comment

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Scroll to Top
×