
Ilé ẹjọ́ tí ó ga jù lọ tí a mọ̀ sí Supreme Court ti fi ọwọ́ òsi da ẹjọ́ tí àwọn ìjọba ìpínlẹ̀ nilé wa pe tako agbára àjọ EFCC láti fi páńpẹ́ ọba gbé ẹni yòówù tó bá pa owó ìlú ní Póńpó.
Nígbà tí ó ń gbé ẹjọ kalẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ náà, Adájọ́ Uwani Abba Aji tí ó léwáju àwọn adájọ́ yòókù ní ẹjọ́ náà kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ rárá.Ó wá fi ọwọ́ méjèèjì dà á nù.Agbẹjọ́rò àgbà ní ìpínlẹ̀ Kogi ló pe agbẹjọ́rò àgbà nile wa lẹ́jọ́ lórí ọ̀rọ̀ náà.
Ìjọba Olóyè Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ ló dá àjọ EFCC,ICPC àtàwon bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ silẹ nígbà tó wà lórí àlèéfà.

Oyè Oyèdọ̀tun jẹ́ gbajúgbajà Agbóhùnsáfẹ́fẹ́ Oníròyìn,Akéwì,Olórin,Ọ̀ǹkọ̀wé, àti Ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn.Ìfẹ́ rẹ̀ sí iṣẹ́ ìròyìn àti èdè Yorùbá ló fa ìdásílẹ̀ ìkànnì yìí.A ti fi ìkòkò ṣe ọbẹ̀,ó yá ẹ je ká tọ́ ọ wò..Oyinmọmọ!

Thanks sir. Ekuse