
Ògbóǹtarìgì Oníwáàsí Àgbáyé Nnì, Muhideen Àjàní Bello ti di olóògbé.Ohun pàtó tó fa ikú olóògbé náà kò ti fi ojú léde.Ẹni ọdún merinlélọ́gọ́rin ni bàbá náà
Ọdún 1940 ni wọn bí Muhideen Àjàní Bello ní ìlú Ìbàdàn. Ó kan ẹ̀kọ́ ìmọ̀ nípa Kùráni,o sì gba ibè di oníwáàsí Àgbáyé.Ó kó ipa takuntakun láti tan ẹ̀sìn islam káàkiri àgbáyé.
Ọ̀kan pàtàkì nínú àwọn oníwáàsí tí a mọ̀ sí Aríbidésí lo túfọ̀ ikú bàbá náà nínú àtẹ̀jáde kan tó gba ìkànnì abẹ́yẹfò X rẹ̀.
Gbogbo àwọn ènìyàn, pàápàá jùlọ ìran Yorùbá kò lè gbàgbé Muideen Bello fún ipa tó kó nínú ìtànkálẹ̀ ẹ̀sìn islam.

Oyè Oyèdọ̀tun jẹ́ gbajúgbajà Agbóhùnsáfẹ́fẹ́ Oníròyìn,Akéwì,Olórin,Ọ̀ǹkọ̀wé, àti Ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn.Ìfẹ́ rẹ̀ sí iṣẹ́ ìròyìn àti èdè Yorùbá ló fa ìdásílẹ̀ ìkànnì yìí.A ti fi ìkòkò ṣe ọbẹ̀,ó yá ẹ je ká tọ́ ọ wò..Oyinmọmọ!
