Ẹ jayé Òní Níttorí Ẹ Ò Mẹ̀yìn Ọ̀la… Babádé

Àlùfáà J.O Babádé

Àlùfáà àgbà tí ìjọ ECWA Omu-Aran, Rev’d J.O Babádé ti sọ yanya pé dandan ni ikú àti pé Àwayeiku kan kò sí fún gbogbo ènìyàn.Òní ni ìríjú Ọlọ́run yìí sàlàyé gbólóhùn yìí nibi ayẹyẹ ìsìnkú mòmò Comfort Oyelaran Olawuyi tó wáyé ní ìjọ ECWA, Òkò loni-in ọjọ́ Jímọ̀n-ọ̀n ojọ́ kejidinlogun osù kẹwàá ọdún yìí.

Ènìyàn Ọlọ́run náà ṣe àlàyé pé kò sí adùn kan láyé yìí ju kí á jẹ́ ẹnìyàn Ọlọ́run,kí á sí ṣe oore tó ní Álùbáríkà fún àwọn ènìyàn lọ.

Olóògbé Comfort Oyelaran Olawuyi

Ó tẹ̀ síwájú pé kò sí ìrọ̀rùn kan láyé ju pé kí á jẹ́ olódodo àti olóòótọ sí àwọn ìlànà àti  àṣẹ Olúwa lọ

Ọdún 2033 ni a bí Comfort Oyelaran Olawuyi, ó lo àádọ́rùn-ún ọdún láyé kò tó di pé ikú pa ojú rẹ̀ dé.

Leave a Comment

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Scroll to Top
×