Nítorí owó tó ná lójú agbo lọ́jọ́ ìgbéyàwó rẹ̀, Abdullahi Musa Hussein dèrò ẹ̀wọ̀n.

Òdodo ni ọ̀rọ̀ àwọn àgbàlagbà tó sọ pé Aburú àti Ire dìjọ ń rìn ni àti pé ìbànújẹ òhun ayọ̀ kò jinná sí ara wọn.Ọ̀rọ̀ yìí ló wà ní ìbámu pẹlú bí ayọ̀ ọkọ ìyàwó kan ní Kano ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Abdullahi Musa Hussein ṣe pàdé ìbànújẹ́ lọ́nà: Ó rí ẹ̀wọ̀n he,Ó sì ti inú òmìnira bọ́ sí inú ìdè .

Ohun tó ṣẹlẹ̀ ní pé àjọ EFCC ló fi páńpẹ́ ọba gbé Hussein látàri pé o fí ojú owó náírà ilẹ̀ wa rí rẹ́dẹrẹ̀dẹ ,ó fi àbùkù kàn án,ó yẹ̀yẹ̀ rẹ̀ pèlú nígbà tí ó ń jó ní gbọ̀ngàn ayẹyẹ Ali Jita Every Centre tó wà ní ìlú Kano ní ọjọ́ kẹfà oṣù Kejìlá ọdún 2024.

Nígbà tó ń rojọ́ nínú Kóòtù, aṣojú ìjọba,Zarami Mohammed ní Hussein ṣe owó tó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún náírà báṣubàṣu eléyìí tó tako abala kọkàndínlógún òfin Báǹkì àpapọ̀ ilẹ̀ wa, eléyìí tí ìjìyà tó dógbin sì wà fún.

Adájọ́ S.M Shuaibu wá bi í léèrè bóyá ó jẹ̀bi tàbí kò jẹ̀bi.Kíá ni òun náà sì ti gbà pé òun jẹ̀bi .

Ìdí rèé ti Adájọ Shuaibu fi rán an ní ẹ̀wọ̀n oṣù mẹ́fà láìsí ànfàní láti san owó ìtanràn.

Bí a kò bá ní gbàgbé, àwọn ènìyàn ńláńla náà ti káwọ́ pànyìn rojọ́ lórí ẹ̀ṣùn ìmẹ́ẹ́rí owó náírà.Lára wọ́n ni Bobrisky,Cubana chief  Priest,Simi Gold àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ.

Leave a Comment

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Scroll to Top
×